Jeremiah 49:7-22

Àsọtẹ́lẹ̀ Ní ti Edomu

7 aNípa Edomu:

Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

“Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani?
Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè?
Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8Yípadà kí o sálọ, sápamọ́ sínú ihò,
ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani,
nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau,
ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá;
ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀?
Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní
kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò,
èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn,
nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́.
Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti
àwọn ará ilé rẹ yóò parun.
Wọn kò sì ní sí mọ́.
11Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀
èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn.
Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un. 13Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”

14Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
A rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé,
Ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.

15“Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di
kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo;
ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú
ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ;
ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta,
tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga
síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì;
láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,”
ni Olúwa wí.
17“Edomu yóò di ahoro
gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì
fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ
18Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu
àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú
tí ó wà ní àyíká rẹ,”
Olúwa wí.
“Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀;
kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.

19“Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá,
Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá.
Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀?
Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí?
Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”

20Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí
Olúwa ní fún Edomu, ohun tí
ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani.
Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde.
Pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn,
a ó gbọ́ igbe wọn
ní Òkun pupa.
22Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀,
yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra.
Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun
Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
Copyright information for YorBMYO